Róòmù 13:4-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Nítorí ìránṣẹ́ Ọlọ́run ni láti ṣe ọ́ ní rere. Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣé nǹkan búburú, máa bẹ̀rù, nítorí kò ru idà náà lásán. Nítorí ìránṣẹ́ Ọlọ́run nííse, ìránṣẹ́ ìbínú sí ara àwọn ẹni tí ń ṣe búburú.

5. Nítorí náà, ó ṣe pàtàkì láti tẹríba fún àwọn alásẹ, kì í ṣe nítorí ìjìyà tó lé wáyé nìkan, ṣùgbọ́n nítorí ẹ̀rí-ọkàn pẹ̀lú.

6. San owó orí rẹ pẹ̀lú nítorí ìdí méjì pàtàkì tí a ti sọ wọ̀nyí. Nítorí pé ó se dandan kí a san owó oṣù fún àwọn òṣìṣẹ́ ìjọba. Èyí yóò mú kí wọn tẹ̀ṣíwájú nínú iṣẹ́ Ọlọ́run náà. Wọn yóò sì máa tọ́jú yín.

7. Ẹ san ohun tí ó tọ́ fún ẹni gbogbo: owó-orí fún ẹni tí owó-orí tọ́ sí: owó-bodè fún ẹni tí owó-bodè tọ́ sí: ẹ̀rù fún ẹni tí ẹ̀rù ń ṣe tirẹ̀; ọlá fún ẹni tí ọlá ń ṣe tirẹ̀

8. Ẹ má ṣe jẹ ẹnikẹ́ní nígbésè, yàtọ̀ fún gbésè ìfẹ́ láti fẹ́ ọmọ ẹnìkejì ẹni, nítorí ẹni tí ó bá fẹ́ ọmọnìkejì rẹ̀, ó kó òfin já.

9. Àwọn òfin, “Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panságà,” “Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn,” “Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè,” “Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké,” bí òfin mìíràn bá sì wà, ni a papọ̀ sọ̀kan nínú òfin kan yìí: “Fẹ́ ọmọnìkejì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ̀.”

Róòmù 13