Róòmù 10:18-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Ṣùgbọ́n mo ní, wọn kò ha gbọ́ bí? Bẹ́ẹ̀ ni nítòótọ́:“Ohùn wọn jáde lọ sí gbogbo ilẹ̀,àti ọ̀rọ̀ wọn sí òpin ayé.”

19. Ṣùgbọ́n mo wí pé, Ísírẹ́lì kò ha mọ̀ bí? Mósè ni ó kọ́ wí pé,“Èmi ó fi àwọn tí kì í ṣe ènìyàn mú yín jowú.Àti àwọn aláìmòye ènìyàn ni èmi ó fi bí yín nínú.”

20. Ṣùgbọ́n Ìsáià tilẹ̀ láyà, ó wí pé,“Àwọn tí kò wá mi rí mi;Àwọn tí kò béèrè mi ni a fi mí hàn fún.”

21. Ṣùgbọ́n nípa ti Ísírẹ́lì ni ó wí pé,“Ní gbogbo ọjọ́ ni mo na ọwọ́ mi sí àwọnaláìgbọ́ràn àti aláríwísí ènìyàn.”

Róòmù 10