Òwe 3:8-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Èyí yóò mú ìlera fún ara à rẹàti okun fún àwọn egungun rẹ.

9. Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa,pẹ̀lú àkọ́so oko ò rẹ

10. Nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnyaàgbá rẹ yóò kún à kún wọ́ sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.

11. Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwamá si ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,

12. Nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wíbí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.

13. Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀,ẹni tí ó tún ní òye síi

14. Nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.

15. Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ;kò sí ohunkohun tí a lè fi wé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.

16. Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀;ní ọwọ́ òsì rẹ̀ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.

Òwe 3