Òwe 24:15-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Má ṣe ba ní ibùba bí i arúfin dé ilé Olódodo,má ṣe kó ibùgbé è rẹ̀ lọ;

16. Nítorí bí olódodo ènìyàn bá tilẹ̀ ṣubú ní ìgbàméje, yóò tún padà dìde ṣáá ni,ṣùgbọ́n ìdàámú yóò fa ènìyàn búburú lulẹ̀.

17. Má ṣe yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú;nígbà tí ó bá kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yọ̀

18. àìṣe bẹ́ẹ̀ Olúwa yóò rí i yóò sì bínúyóò sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.

19. Má ṣe fòyà nítorí àwọn ènìyàn ibitàbí jowú àwọn ènìyàn búburú,

20. nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájúa ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.

Òwe 24