Òwe 23:9-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Má ṣe sọ̀rọ̀ ní etí aṣiwèrè (òmùgọ̀);nítorí tí yóò gan ọgbọ́n ọ̀rọ̀ rẹ.

10. Má ṣe sí ààlà àtijọ́ kúrò;má sì ṣe bọ́ sínú oko aláìní baba.

11. Nítorí pé Olùràpadà wọn lágbára;yóò gba ìjà wọn jà sí ọ.

12. Fi àyà sí ẹ̀kọ́,àti etí rẹ sí ọ̀rọ̀ ìmọ̀.

13. Má ṣe fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kúrò lára ọmọdé,nítorí pé bí ìwọ bá fi pàṣán nà án, òun kì yóò kú.

14. Bí ìwọ fi pàṣán nà án,ìwọ ó sì gbà ọkàn rẹ̀ là kúrò ní ọ̀run-àpáàdì.

15. Ọmọ mi, bí ọkàn rẹ bá gbọ́n,ọkàn mi yóò yọ̀, àní èmi pẹ̀lú.

16. Inú mi yóò sì dùn nígbà tí ètè rẹ̀ bá ń sọ̀rọ̀ títọ́.

17. Má ṣe jẹ́ kí àyà rẹ ó ṣe ìlara sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,ṣùgbọ́n kí ìwọ ó wà ní ìbẹ̀rù Olúwa,ní ọjọ́ gbogbo.

Òwe 23