Òwe 23:25-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Jẹ́ kí bàbá rẹ àti ìyá rẹ ó yọ̀,sì jẹ́ kí inú ẹni tí ó bí ọ dùn.

26. Ọmọ mi, fi àyà rẹ fún mi,kí o sì jẹ́ kí ojú rẹ ní inú-dídùn sí ọ̀nà mi.

27. Nítorí pé panṣágà-obìnrin ọ̀gbun jínjìn ni;àti àjèjì-obìnrin kànga híhá ni.

28. Òun á sì ba ní bùba bí olè,a sì sọ àwọn olùrékọjá di púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn.

29. Ta ni ó ni òsì? Ta ni ó ni ìbànújẹ́?Ta ni ó ni ìjà? Ta ni ó ni aṣọ̀? Ta ni ó ni ọgbẹ́ láìnídìí?

30. Àwọn tí ó dúró pẹ́ níbi ọtí-wáìnì;àwọn tí ń lọ láti dán ọtí wáìnì àdàlú wò.

Òwe 23