Òwe 21:27-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. Ẹbọ ènìyàn búburú, ìríra ni:mélòómélòó ni nígbà tí ó mú un wá pẹ̀lú èrò ìwà-ibi?

28. Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé:ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ẹni tí ó gbọ́, yóò dúró.

29. Ènìyàn búburú mú ojú ara rẹ̀ le:ṣùgbọ́n ẹni ìdúró-ṣinṣin ni ó ń mú ọ̀nà rẹ̀ tọ́.

30. Kò sí ọgbọ́n, kò sí ìmòye,tàbí ìmọ̀ràn tí ó le mókè níwájú Olúwa.

31. A ń múra ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun:ṣùgbọ́n ìṣẹ́gun jẹ́ ti Olúwa.

Òwe 21