Òwe 15:12-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Ẹlẹ́gàn kórìíra ìbáwí:kò ní gbàmọ̀ràn lọ́dọ̀ ọlọ́gbọ́n.

13. Inú dídùn máa ń mú kí ojú túkáṣùgbọ́n ìbànújẹ́ ọkàn máa ń pa ẹ̀mí run.

14. Ọkàn olóye ń wá ìmọ̀ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n ń fẹ́ ìwà òmùgọ̀ bí ẹní jẹun.

15. Gbogbo ọjọ́ àwọn olùpọ́njú jẹ́ ibi,ṣùgbọ́n ọkàn tí ń dunnú a máa Jàṣè ṣáá.

16. Ó sàn kí ó má pọ̀, kí ìbẹ̀rù Olúwa sì wàju ọrọ̀ púpọ̀ pẹ̀lú ìyọnu.

17. Oúnjẹ ewébẹ̀ níbi tí ìfẹ́ wàsàn ju àbọ́pa màlúù tòun ti ìríra.

18. Ènìyàn onínú ríru dá ìjà sílẹ̀ṣùgbọ́n onísùúrù paná ìjà.

19. Ẹ̀gún dí ọ̀nà ọ̀lẹṣùgbọ́n pópónà tí ń dán ni ti àwọn dídúró ṣinṣin.

Òwe 15