Òwe 14:32-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

32. Nígbà tí ìyọnu bá dé, a fa àwọn búburú lulẹ̀,kódà nínú ikú àwọn olódodo ni ààbò.

33. Ọgbọ́n wà nínú ọkàn olóyekódà láàrin àwọn aláìlóye, ó jẹ́ kí wọn mọ òun.

34. Ododo a máa gbé orílẹ̀ èdè ga,ṣùgbọ́n ìtìjú ni ẹ̀ṣẹ̀ jẹ́ fún àwùjọ káwùjọ.

35. Ọba a máa ní inú dídùn sí ìránṣẹ́ tí ó gbọ́nṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ wá sórí ìránṣẹ́ adójútini.

Òwe 14