Òwe 14:21-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Ẹni tí ó kẹ́gàn aládùúgbò o rẹ̀ ti dẹ́ṣẹ̀ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ẹni tí ó ṣàánú àwọn aláìní.

22. Ǹjẹ́ àwọn tí ń pète ibi kì í sìnà?Ṣùgbọ́n àwọn tí ń gbérò ohun rere ń rí ìfẹ́ àti òtítọ́.

23. Gbogbo iṣẹ́ àṣekára ló máa ń mú èrè wáṣùgbọ́n ẹjọ́ rírò lásán máa ń ta ni lósì ni.

24. Ọrọ̀ Ọlọgbọ́n ènìyàn ni adé orí wọnṣùgbọ́n ìwà aláìgbọ́n ń mú ìwà òmùgọ̀ wá.

25. Ẹlẹ́rìí tí ó ṣòótọ́ gba ẹ̀mí làṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí èké jẹ́ ẹlẹ́tàn.

26. Ẹni tí ó bẹ̀rù Olúwa ni ilé ìṣọ́ ààbòyóò sì tún jẹ́ ààbò fún àwọn ọmọ rẹ̀.

27. Ìbẹ̀rù Olúwa jẹ́ oríṣun ìyè,tí ń yí ènìyàn padà kúrò nínú ìkẹ́kùn ikú.

28. Ènìyàn púpọ̀ ní ìlú jẹ́ ògo Ọba,ṣùgbọ́n láì sí ìjòyè, Ọba á parun.

Òwe 14