Orin Sólómónì 2:4-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ó mú mi lọ sí ibi gbọ̀ngàn àṣè,Ìfẹ́ sì ni ọ̀pàgun rẹ̀ lórí mi.

5. Fi agbára adùn àkàrà dá mi dúró.Fi èṣo ápù tù mi láraNítorí àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mí.

6. Ọwọ́ òsì rẹ ń bẹ lábẹ́ orí miỌwọ́ ọ̀tún rẹ sì ń gbà mí mọ́ra

7. Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mù,mo fi abo egbin àti ọmọ àgbọ̀nrín fi yín búKí ẹ má ṣe ru ìfẹ́ olùfẹ́ mi sókèKí ẹ má sì ṣe jí i títí yóò fi wù ú

8. Gbọ́ ohùn olùfẹ́ mi!Wò ó! Ibí yìí ni ó ń bọ̀.Òun ń fò lórí àwọn òkè ńlá,Òun bẹ́ lórí àwọn òkè kékèké

9. Olùfẹ́ mi dàbí abo egbin tàbí ọmọ àgbọ̀nrínWò ó! Níbẹ̀ ni ó wà lẹ́yìn ògiri waÓ yọjú ní ojú fèrèséÓ ń fi ara rẹ̀ hàn lójú fèrèsé ọlọ́nà

10. Olùfẹ́ mi fọhùn ó sì sọ fún mi pé,“Dìde, Olùfẹ́ mi,Arẹwà mi, kí o sì wà pẹ̀lú mi.

11. Wò ó! Ìgbà otútù ti kọjá;Òjò ti rọ̀ dawọ́, ó sì ti lọ.

12. Àwọn òdòdó fara hàn lórí ilẹ̀Àsìkò ìkọrin àwọn ẹyẹ déA sì gbọ́ ohùn àdàbà ní ilẹ̀ wa.

Orin Sólómónì 2