Oníwàásù 6:8-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Kí ni àǹfàní tí ọlọgbọ́n ènìyàn nílórí aṣiwèrè?Kí ni èrè talákà ènìyànnípa mímọ bí yóò ṣe hùwà níwájú àwọn tó kù?

9. Ohun tí ojú rí sànju ìfẹnúwákiri lọAṣán ni eléyìí pẹ̀lúó dàbí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́.

10. Ohunkóhun tí ó bá ti wà ti ní orúkọ,ohun tí ènìyàn jẹ́ sì ti di mímọ̀;kò sí ènìyàn tí ó le è ja ìjàkadìpẹ̀lú ẹni tí ó lágbára jùú lọ

11. Ọ̀rọ̀ púpọ̀,kì í ní ìtumọ̀èrè wo ni ènìyàn ń rí nínú rẹ̀?

12. Àbí, ta ni ó mọ ohun tí ó dára fún ènìyàn ní ayé fún ọjọ́ ayé kúkúrú àti aṣán tí ó ń là kọjá gẹ́gẹ́ bí òjìji? Ta ni ó le è sọ fún mi, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ lábẹ́ oòrùn lẹ́yìn tí ó bá lọ tán? kò sí!

Oníwàásù 6