Onídájọ́ 5:2-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. “Nítorí bí àwọn olórí ti ṣíwájú ní Ísírẹ́lì,nítorí bi àwọn ènìyàn ti fi tọkàntọkàn wa,Ẹ fi ìbùkún fún Olúwa!

3. “Ẹ gbọ́ ẹ̀yin ọba! Ẹ̀yin ìjòyè!Èmi yóò kọrin nípa Olúwa, èmi yóò kọrinÈmi yóò kọrin sí Olúwa: Ọlọ́run Ísírẹ́lì.

4. “Olúwa nígbà tí o jáde lọ láti Ṣéírì,nígbà tí o yan láti ilẹ̀ Édómù,ilẹ̀ mì tìtì, àwọn ọ̀run ya,ìkúùkù àwọ̀sámọ̀ da omi wọn sílẹ̀.

5. Àwọn òkè mì tìtì ní iwájú Olúwa Ísírẹ́lì ẹni tí ó ni Ṣínáì,níwájú Olúwa ẹni mímọ́ Ísírẹ́lì.

6. “Ní àwọn ọjọ́ Ṣámgárì ọmọ Ánátì,Ní àwọn ọjọ́ Jáélì, a kọ àwọn ojú ọ̀nà sílẹ̀;àwọn arìnrìnàjò ń gba kọ̀rọ̀ kọ́rọ́.

Onídájọ́ 5