Onídájọ́ 5:11-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. ariwo àwọn tafàtafà, ní ibi tí a gbé ń fa omi.Wọ́n ń sọ ti iṣẹ́ òdodo Olúwa níbẹ̀,àní iṣẹ òdodo ìjọba rẹ̀ ní Ísírẹ́lì.“Nígbà náà ni àwọn ènìyàn Olúwasọ̀ kalẹ̀ lọ sí ibodè.

12. ‘Jí, jí, Dèbórà!Jí, jí, kó orin dìde!Dìde Bárákì!Kó àwọn ìgbékùn rẹ ní ìgbékùn ìwọ ọmọ Ábínóámù.’

13. “Nígbà náà ni ó fi àwọn tókùjọba lórí àwọn ènìyàn; Olúwa fún mi ìjọbalórí àwọn alágbára.

14. Àwọn kan jáde wá láti Éfúráímù, àwọn tí gbòǹgbò wọn wà ní Ámélékì;Bẹ́ńjámínì wà pẹ̀lú àwọn tí ó tẹ̀lé ọ.Láti Mákírì ni àwọn alásẹ ti sọ̀ kalẹ̀ wá,láti Ṣébúlúnì ni àwọn ẹni tí ń mú ọ̀pá oyè lọ́wọ́.

Onídájọ́ 5