1. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì Ísírẹ́lì kò ní ọba.Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Léfì tí ń gbé ibi tí ó sápamọ́ nínú àwọn agbégbé òkè Éfúráímù, mú àlè kan láti Bẹ́tílẹ́hẹ́mù ní Júdà.
2. Ṣùgbọ́n àlè rẹ̀ náà jẹ́ aláìṣòótọ́ sí i, òun fi sílẹ̀, ó sì padà lọ sí ilé baba rẹ̀ ní Bẹ́tílẹ́hẹ́mù ti Júdà. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti lo oṣù mẹ́rin ní ilé baba rẹ̀
3. ọkọ rẹ̀ lọ sí ibẹ̀ láti rọ̀ ọ́ pé kí ó padà sí ọ̀dọ̀ òun. Nígbà tí ó ń lọ ó mú ìránṣẹ́ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì lọ́wọ́, obìnrin náà mú un wọ inú ilé baba rẹ̀ lọ, nígbà tí baba obìnrin náà rí i ó fi tayọ̀ tayọ̀ gbà á.