Onídájọ́ 16:29-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Sámúsónì sì na ọwọ́ mú àwọn òpó méjèèjì tí ó wà láàárin gbùngbùn, orí àwọn tí tẹ́ḿpìlì náà dúró lé, ó fi ọwọ́ ọ̀tún mú ọ̀kan àti ọwọ́ òsì mú èkejì, ó fi ara tì wọ́n,

30. Sámúsónì sì wí pé, “Jẹ́ kí èmi kú pẹ̀lú àwọn Fílístínì!” Òun sì fi agbára ńlá tì wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni ilé náà wó lu àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn tí ó wà nínú rẹ̀. Báyìí ni ó pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nígbà ikú rẹ̀ ju ìgbà ayé rẹ̀ lọ.

31. Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ ní àpapọ̀ gòkè lọ wọ́n sì gbé e, wọ́n gbé e padà wá, wọ́n sì sin ín sí agbede-méjì Sórà àti Ésítaólì sínú ibojì Mánóà baba rẹ̀. Òun ti ṣe àkóso Ísírẹ́lì ní ogún (20) ọdún.

Onídájọ́ 16