Nọ́ḿbà 33:40-49 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

40. Àwọn ará Kénánì, ọba Árádì, tí ń gbé ìhà gúṣù ní ilẹ̀ Kénánì gbọ́ pé àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń bọ̀.

41. Wọ́n kúrò ní orí òkè Hórì, wọ́n sì pàgọ́ ní Ṣálímónà.

42. Wọ́n kúrò ní Ṣálímónà wọ́n sì pàgọ́ ní Púnónì.

43. Wọ́n kúrò ní Púnónì wọ́n sì pàgọ́ ní Óbótù.

44. Wọ́n kúrò ní Óbótù wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Ábárímù, ní agbégbé Móábù.

45. Wọ́n kúrò ní Íyímù wọ́n sì pàgọ́ ní Díbónì-Gádì.

46. Wọ́n kúrò ní Dibónì-Gádì wọ́n sì pàgọ́ ní Alimoni-Díbílátamù.

47. Wọ́n kúrò ní Alimoni-Díbílátaímù wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Ábárímù lẹ́bá Nébò.

48. Wọ́n kúrò ní orí òkè Ábárímù wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Móábù lẹ́bá Jọ́dánì ní ìkọjá Jẹ́ríkò.

49. Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Móábù wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jọ́dánì láti Bẹti-Jéíóù títí dé Abeli-Sítímù

Nọ́ḿbà 33