14. Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ kò bá sọ nǹkan kan sí í nípa rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́, nígbà náà ni ó se ìwádí nípa ẹ̀jẹ́ àti ìbúra ìdè tí ó dè é. Kí ọkùnrin náà se ìwádìí lórí rẹ̀ láì sọ nípa rẹ̀ si nígbà tí ó gbọ́ nípa rẹ̀.
15. Bí ó ti wù kí ó rí, bí ọkùnrin náà bá sọ ọ́ dasán, ní àkókò kan lẹ́yín tí ó ti gbọ́ wọn, nígbà náà ó jẹ̀bi ọ̀rọ̀ náà.”
16. Èyí ni ìlànà tí Olúwa fún Mósè nípa ìbátan láàrin ọkùnrin àti obìnrin àti láàrin baba àti ọ̀dọ́mọbìnrin rẹ̀ tí ó sì ń gbé ní ilé rẹ̀.