Nọ́ḿbà 27:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Tí kò bá ní ọmọbìnrin, fi ohun ìní rẹ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀.

10. Tí kò bá ní arakùnrin, fi ogún ìní rẹ̀ fún arákùnrin baba rẹ̀.

11. Tí baba rẹ̀ kò bá ní arákùnrin, fún ará ilé rẹ̀ tí ó bá súnmọ́ jù ní ìdílé rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀, kí ó lè jogún rẹ̀. Èyí gbọdọ̀ jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti paláṣẹ fún Mósè.’ ”

12. Nígbá náà Olúwa sọ fún Mósè pé, “Lọ sì orí òkè Ábárímù yìí, kí o sì lọ wo ilẹ̀ tí mo fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.

13. Lẹ́yìn ìgbà tí o bá sì ti rí i, ìwọ náà yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ gẹ́gẹ́ bí Árónì arákùnrin rẹ ṣe ṣe,

Nọ́ḿbà 27