Nọ́ḿbà 26:46-51 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

46. (Orúkọ ọmọ Áṣérì obìnrin nì jẹ́ Ṣérà.)

47. Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Áṣérì gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbéje (53,400).

48. Ti àwọn ọmọ Náfítalì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:ti Jásélì, ìdílé àwọn ọmọ Jásélì:ti Gúnì, ìdílé àwọn ọmọ Gúnì;

49. ti Jésérì, ìdílé àwọn ọmọ Jéṣérì;ti Ṣílémù, ìdílé àwọn ọmọ Ṣilemù.

50. Wọ̀nyí ni ìdílé ti Náfítalì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé egbéje (45,400).

51. Àpapọ̀ iye tí a kà nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́, ó lé ẹgbẹ̀sán ó dín àádọ́rin (601,730).

Nọ́ḿbà 26