Nọ́ḿbà 26:28-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Àwọn ọmọ Jósẹ́fù gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; Mánásè àti Éfúráímù:

29. Àwọn ọmọ Mánásè:ti Mákírì, ìdílé Mákírì (Mákírì sì bí Gílíádì);ti Gílíádì, ìdílé àwọn ọmọ Gílíádì.

30. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gílíádì:ti Íésérì, ìdílé Íésérì;ti Hélékì, ìdílé Hélékì

31. àti ti Ásíríẹ́lì, ìdílé Ásíríẹ́lì;àti ti Ṣékémù, ìdílé Ṣékémù;

32. àti Ṣemídà, ìdílé àwọ ọmọ Ṣemídà;àti ti Heférì, ìdílé àwọn ọmọ Héférì.

33. (Selofehádì ọmọ Héférì kò sì ni ọmọkùnrin, bí kò ṣe ọmọbìnrin; orúkọ àwọn ọmọbìnrin Selofehádì ni Málà, Nóà, àti Hógílà, Mílíkà àti Táṣà).

34. Wọ̀nyí ni ìdílé Mánásè tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàámẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin (52,700).

Nọ́ḿbà 26