24. Kàkà bẹ́ẹ̀, mo fún àwọn ọmọ Léfì gẹ́gẹ́ bí ogún wọn, ìdá kan nínú ìdá mẹ́wàá tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pèsè gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa. Èyí ni mo wí nípa wọn: Wọn kò ní gba ogún kankan láàrin àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.”
25. Olúwa sọ fún Mósè pé,
26. “Sọ fún àwọn ọmọ Léfì kí o sì wí fún wọn pé: ‘Nígbà tí ìdámẹ́wàá bá ń wọlé láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí ogún rẹ. O gbọdọ̀ mú ìdámẹ́wàá lára rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ Olúwa.