17. Kí ẹnì kọ̀ọ̀kan yín mú àwo tùràrí, kí ó sì fi tùràrí sínú rẹ̀, kí gbogbo rẹ̀ jẹ́ àádọ́tàlénígba àwo tùràrí (250) kí ẹ sì ko wá ṣíwájú Olúwa. Ìwọ àti Árónì yóò mú àwo tùràrí wá pẹ̀lú.”
18. Nígbà náà ni oníkálukú wọn mú àwo tùràrí, wọ́n fi iná àti tùràrí sí i nínú, wọ́n sì dúró sí ẹnu ọ̀nà Àgọ́ Ìpàdé, àwọn pẹ̀lú Mósè àti Árónì.
19. Nígbà tí Kórà kó gbogbo àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ jọ sí ẹnu ọ̀nà Àgọ́ Ìpàdé, ògo Olúwa sì farahan gbogbo ìjọ ènìyàn.
20. Olúwa sì sọ fún Mósè àti Árónì pé,