Nọ́ḿbà 13:3-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Mósè sì rán wọn jáde láti Aginjù Páránì gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa. Gbogbo wọn jẹ́ olórí àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì.

4. Orúkọ wọn nìwọ̀nyí:láti inú ẹ̀yà Rúbẹ́nì Ṣámuá ọmọ Ṣákúrì;

5. láti inú ẹ̀yà Símónì, Ṣáfátì ọmọ Hórì;

6. láti inú ẹ̀yà Júdà, Kélẹ́bù ọmọ Jéfúnè;

7. Láti inú ẹ̀yà Ísíkárì, Ígálì ọmọ Jósẹ́fù;

8. Láti inú ẹ̀yà Éfúráímù, Ósíà ọmọ Núnì;

9. Láti inú ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì, Pálítì ọmọ Raù;

10. Láti inú ẹ̀yà Ṣébúlónì, Gádíélì ọmọ Ṣódì;

11. Láti inú ẹ̀yà Mánásè, (ẹ̀yà Jósẹ́fù), Gádì ọmọ Ṣúsì;

12. Láti inú ẹ̀yà Dánì, Ámíélì ọmọ Gémálì;

13. Láti inú ẹ̀yá Áṣérì, Ṣétúrì ọmọ Míkáẹ́lì.

14. Láti inú ẹ̀yà Náfítanì, Nábì ọmọ Fófósì;

15. Láti inú ẹ̀yà Gádì, Géúlì ọmọ Mákì.

16. Wọ̀nyí ni orukọ àwọn ènìyàn tí Mósè rán láti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò. (Ósísà ọmọ Núnì ni Mósè sọ ní Jóṣúà.)

Nọ́ḿbà 13