27. Wọ́n sì fún Mósè ní ìròyìn báyìí: “A lọ sí ilẹ̀ ibi tí o rán wa, lóótọ́ ló sì ń sàn fún wàrà àti fún oyin! Èṣo ibẹ̀ nìyìí.
28. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tó ń gbé níbẹ̀ lágbára, àwọn ìlú náà jẹ́ ìlú olódi bẹ́ẹ̀ ni ó sì tóbi púpọ̀. A tilẹ̀ rí àwọn irú ọmọ Ánákì níbẹ̀.
29. Àwọn Ámálékì ń gbé ní ilẹ̀ Gúsù; àwọn ará Hítì, àwọn ará Jébúsì àti àwọn ará Ámórì ni wọ́n ń gbé ní orí òkè ilẹ̀ náà, àwọn ará Kénánì sì ń gbé ẹ̀bá òkun àti ní etí bèbè Jọ́dánì.”
30. Kélẹ́bù sì pa àwọn ènìyàn náà lẹ́nu mọ́ níwájú Mósè, ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á gòkè lọ lẹ́ẹ̀kan náà láti lọ gba ilẹ̀ náà, nítorí pé àwa le è gbà á.”