Nọ́ḿbà 11:5-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Àwa rántí ẹja tí à ń jẹ lọ́fẹ̀ẹ́ ní Éjíbítì, apálá, ègúsí, ewébẹ̀ àlùbọ́sà àti àwọn ẹ̀fọ́ mìíràn

6. Ṣùgbọ́n báyìí gbogbo ara wa ti gbẹ, kò sí ohun mìíràn láti jẹ àfi mánà nìkan tí a rí yìí!”

7. Mánà náà dàbí èso koriáńdérì, ìrísí rẹ̀ sì dàbí oje igi.

8. Àwọn ènìyàn náà ń lọ káàkiri láti kó o, wọn ó lọ̀ ọ́ lórí ọlọ tàbí kí wọ́n gún un nínú odó. Wọ́n le ṣè é nínú ìkòkò tàbí kí wọn ó fi ṣe àkàrà, adùn rẹ̀ yóò sì dàbí adùn ohun tí a fi òróró ṣe.

9. Nígbà tí ìrì bá ṣẹ̀ sí ibùdó lórí ni mánà náà máa ń bọ́ pẹ̀lú rẹ̀.

10. Mósè sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sunkún ní gbogbo ìdílé wọn, oníkálukú ní ẹnu ọ̀nà àgọ́ tirẹ̀. Olúwa sì bínú gidigidi. Inú Mósè sì bàjẹ́ pẹ̀lú.

Nọ́ḿbà 11