33. Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹran náà sì wà láàrin eyín wọn, kó tó di pé wọ́n jẹ ẹ́, ìbínú Olúwa sì ru sí àwọn ènìyàn, ó sì pa wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-àrùn.
34. Torí èyí ni wọ́n ṣe pe ibẹ̀ ní Kíbírótì Hátafà nítorí pé níbẹ̀ ni wọ́n gbé sìnkú àwọn ènìyàn tó ní ọ̀kánjúà oúnjẹ sí.
35. Àwọn ènìyàn yóòkù sì gbéra láti Kíbírótì Hátafà lọ pa ibùdó sí Hásérótì wọ́n sì dúró nibẹ̀.