Nehemáyà 9:7-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. “Ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run, tí ó yan Ábúrámù tí ó sì mú u jáde láti Úrì ti Kálídéà, tí ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Ábúráhámù.

8. Ìwọ sì rí í pé ọkàn rẹ̀ jẹ́ olóòótọ́ sí ọ, ìwọ sì dá májẹ̀mú pẹ̀lú u rẹ̀ láti fi ilẹ̀ àwọn aráa Kénánì, Hítì, Ámórì, Pérísì, Jébúsì àti Gírígásì fún irú àwọn ọmọ rẹ̀. Ìwọ ti pa ìpinnu rẹ̀ mọ́ nítorí tí ìwọ jẹ́ olódodo.

9. “Ìwọ rí ìpọ́njú àwọn baba ńlá wa ní Éjíbítì; ìwọ gbọ́ igbe ẹkún un wọn ní òkun pupa.

10. Ìwọ rán iṣẹ́ àmì àti isẹ́ ìyanu sí Fáráò, sí gbogbo àwọn ìjòyèe rẹ̀ àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ ẹ rẹ̀, nítorí ìwọ mọ ìwà ìgbéraga tí àwọn ará Éjíbítì hù sí wọn. Ìwọ ra orúkọ fún araà rẹ, èyí tí ó sì wà títí di òní yìí.

Nehemáyà 9