Mátíù 23:17-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Ẹ̀yin aláìmòye afọ́jú: èwo ni ó ga jù, wúrà tàbí tẹ́ḿpílì tí ó ń sọ wúrà di mímọ́?

18. Àti pé, Ẹmikẹ́ni tó bá fi pẹpẹ búra, kò já mọ́ nǹkan, ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni tí ó ba fi ẹ̀bùn tí ó wà lórí rẹ̀ búra, ó di ajigbèsè.

19. Ẹ̀yin aláìmòye afọ́jú wọ̀nyí! Èwo ni ó pọ̀ jù: ẹ̀bùn tí ó wà lórí pẹpẹ ni tàbí pẹpẹ fúnra rẹ̀ tí ó sọ ẹ̀bùn náà di mímọ́?

20. Nítorí náà ẹnikẹ́ni tí ó bá ń fi pẹpẹ búra, ó fi í búra àti gbogbo ohun tí ó wà lórí rẹ̀.

21. Àti pé, ẹni tí ó bá fi tẹ́mńpílì búra, ó fi í búra àti ẹni tí ń gbé inú rẹ̀.

22. Àti pé, ẹni tí ó bá sì fi ọ̀run búra, ó fi ìtẹ́ Ọlọ́run àti ẹni tí ó jókòó lóri rẹ̀ búra.

23. “Ègbé ni fún yín ẹ̀yin olùkọ́ òfin àti Farisí, ẹ̀yin àgàbàgebè! Nítorí ẹ̀yin ń gba ìdámẹ́wàá míńtì, áníṣè àti kùmínì, ẹ̀yin sì ti fi ohun tí ó ṣe pàtàkì jù lọ nínú òfin sílẹ̀ láìṣe ìdájọ́, àánú àti ìgbàgbọ́: Wọ̀nyí ni ó tọ́ tí ẹ̀yin ìbá ṣe, ẹ̀yin kò bá fi wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀ láìṣe.

24. Ẹ̀yin afọ́jú tó ń afójú mọ̀nà! Ẹ tu kòkòrò tó bọ́ sì yín lẹ́nu nù, ẹ gbé ràkúnmí mì.

25. “Ègbé ni fún yín ẹ̀yin Farisí àti ẹ̀yin olùkọ́ òfin, ẹ̀yin àgàbàgebè. Ẹ̀yin ń fọ òde aago àti àwo ṣùgbọ́n inú rẹ̀ kún fún ìrẹ́jẹ àti ẹ̀gbin gbogbo.

Mátíù 23