27. Nítorí Ọmọ ènìyàn yóò wá nínú ogo baba rẹ pẹ̀lú àwọn ańgẹ́lì rẹ̀, nígbà náà ni yóò sì san án fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.
28. Lóòótọ́ ni mo wí fún yín. Ẹlòmíràn wà nínú àwọn tí ó níhìn-ín yìí, tí kì yóò ri ikú títí wọn ó fi rí ọmọ-ènìyàn tí yóò máa bà ní ìjọba rẹ̀.”