Mátíù 12:15-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ṣùgbọ́n Jésù mọ, ó yẹra kúrò níbẹ̀. Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì mú gbogbo àwọn aláìsàn láradá.

16. Ṣùgbọ́n ó kìlọ̀ fún wọn pé kí wọ́n má ṣe sọ ẹni ti òun jẹ́.

17. Èyí jẹ́ ìmúṣẹ àṣọtẹ́lẹ̀ èyí tí wòlíì Àìsáyà sọ nípa rẹ̀ pé:

18. “Ẹ wo ìránṣẹ mi ẹni tí mo yàn.Àyànfẹ́ mi ni ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi;èmi yóò fi ẹ̀mí mi fún un.Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ orílẹ̀-èdè gbogbo.

19. Òun kì yóò jà. bẹ́ẹ̀ ni kì yóò kígbe;ẹnikẹ́ni kì yóò gbọ́ ohùn rẹ ní ìgboro.

20. Ìyẹ́ tí ó fẹ́rẹ̀ fò ni kí yóò ṣẹ́,bẹ́ẹ̀ ni kì yóò pa iná fìtílà tí ó rú èéfín.Títí yóò fi mú ìdájọ́ dé ìsẹ́gun.

21. Ní orúkọ rẹ̀ ni gbogbo ayé yóò fi ìrètí wọn sí.”

22. Nígbà náà ni wọ́n mú ọkùnrin kan tó ni ẹmí-èṣù tọ̀ ọ́ wá, tí ó afọ́jú, tí ó tún ya odi. Jésù sì mú un lára dá kí ó le sọ̀rọ̀, ó sì ríran.

Mátíù 12