Máàkù 8:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọjọ́ kan, bí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti péjọ, kò sí oúnjẹ fún wọn mọ́ láti jẹ. Jésù pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.

2. Ó wí fún wọn pé, “Àánú ọ̀pọ̀ ènìyàni wọ̀nyí ṣe mí nítorí pé ó tó ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti wà níhìn-ín, kò sì sí ohun kan tí ó kù sílẹ̀ fún wọn láti jẹ.

3. Bí mo bá sọ fún wọn láti máa lọ sí ilé wọn bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ebi, wọn yóò dákú lójú-ọ̀nà, nítorí pé àwọn mìíràn nínú wọn ti ọ̀nà jínjìn wá.”

4. Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ béèrè pé, “Níbo ni a ó ti rí búrẹ́dì tí ó tó láti fibọ wọn nínú aṣálẹ̀ yìí?”

5. Jésù béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ìsù búrẹ́dì mélòó lẹ ní lọ́wọ́?”Wọ́n fèsì pé, “isu búrédì méje.”

6. Nítori náà, ó pàsẹ fún àwọn ènìyàn náà láti jókòó lórí ilẹ̀. Ó sì mú odindi búrédì méje náà, ó dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run, ó sì bù wọ́n sí wẹ́wẹ́, ó pín wọ́n fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti gbé ka iwájú àwọn ènìyàn, wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀.

Máàkù 8