15. àti láti lágbára láti lé àwọn ẹ̀mí Èsù jáde.
16. Wọ̀nyí ni àwọn méjìlá náà tí ó yàn, Ṣímóní (ẹni ti ó sọ àpèlé rẹ̀ ní Pétérù)
17. Jákọ́bù ọmọ Sébédè àti Jòhánù arákùnrin rẹ̀ (àwọn ẹni tí Jésù sọ àpèlé wọ́n ní Bóánájì, èyí tí ó túmọ̀ sí àwọn ọmọ àrá).
18. Àti Ańdérù, Fílípì, Bátólómíù, Mátíù, Tómásì, Jákọ́bù (ọmọ Álíféù), Tádéù, Símónì (ọ̀kan nínú àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú tí ó fẹ́ ará Kénánì tí ó fi ìjàngbọ̀n dojú ìjọba Rómù bolẹ̀)
19. Àti Júdásì Ísíkáríọ́tù, ẹni tí ó fi í hàn níkẹyìn.