Máàkù 11:16-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Kò sì gba ẹnikẹ́ni láàyè láti gbé ẹrù ọjà títa wọlé.

17. Gẹ́gẹ́ bí ó ti kọ́ wọn, ó wí pé, “Ṣe a kò ti kọ ọ́ pé:“ ‘Ilé àdúrà ni a o máa pe ilé mi,ní gbogbo òrilẹ̀ èdè’?Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti sọ ọ́ di ibùgbé àwọn ọlọ́ṣà.”

18. Nígbà tí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́-òfin gbọ́ ohun tí ó ti ṣe, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ń gbà èrò bí wọn yóò ti ṣe pa á. Wọ́n bẹ̀rù rògbòdìyàn tí yóò bẹ́ sílẹ̀, nítorí tí àwọn ènìyàn ní ìgbóná-ọkàn sí ẹ̀kọ́ rẹ̀.

19. Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ náà, bí ìṣe wọn, Jésù àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ jáde kúrò ní ìlú Jerúsálémù.

Máàkù 11