Máàkù 10:49-52 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

49. Nígbà tí Jésù gbọ́ igbe rẹ̀, ó dẹṣẹ̀ dúró lójú-ọ̀nà, ó sì wí pé, “Ẹ pè é kí ó wá sọ́dọ̀ mi.” Nítorí náà wọ́n pe ọkùnrin afọ́jú náà, wọ́n wí pé, “Tújúká!, dìde lórí ẹsẹ̀ rẹ! Ó ń pè ọ́.”

50. Lẹ́sẹ̀kan-náà, Bátíméù bọ́ aṣọ rẹ̀ sọnù, ó fò sókè, ó sì wá sọ́dọ̀ Jésù.

51. Jésù béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ìwọ fẹ́ kí èmi kí ó ṣe fún ọ?”Afọ́jú náà dáhùn pé, “Rábì, jẹ́ kí èmi ki o ríran.”

52. Jésù wí fún un pé, “Má a lọ, ìgbàgbọ́ rẹ ti mú ọ láradá.” Lẹ́ṣẹ̀kẹṣẹ̀, ọkùnrin afọ́jú náà ríran ó sì ń tẹ̀lé Jésù lọ ní ọ̀nà.

Máàkù 10