Lúùkù 4:16-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Ó sì wá sí Násárẹ́tì, níbi tí a gbé ti tọ́ ọ dàgbà: bí ìṣe rẹ̀ ti rí, ó sì wọ inú sínágọ́gù lọ ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì dìde láti kàwé.

17. A sì fi ìwé wòlíì Àìsáyà fún un. Nígbà tí ó sì ṣí ìwé náà, ó rí ibi tí a gbé kọ ọ́ pé:

18. “Ẹ̀mí Olúwa ń bẹ lára mi,Nítorí tí ó fi àmì òróró yàn míláti wàásù ìhìnrere fún àwọn òtòsì.Ó ti rán mi wá láti wàásù ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn, àtiìtúnríran fún àwọn afọ́jú,àti láti jọ̀wọ́ àwọn tí a pa lára lọ́wọ́,

19. Láti kéde ọdún ojúrere Olúwa.”

20. Ó sì pa ìwé náà dé, ó fi í fún ìránṣẹ́, ó sì jókòó. Gbogbo àwọn tí ó ń bẹ nínú sínágọ́gù sì tẹjúmọ́ ọn.

Lúùkù 4