Lúùkù 2:42-48 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

42. Nígbà tí ó sì di ọmọ ọdún méjìlá, wọ́n gòkè lọ sí Jerúsálémù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àjọ náà.

43. Nígbà tí ọjọ́ wọn sì pé bí wọ́n ti ń padà bọ̀, ọmọ náà, Jésù dúró lẹ́yìn ní Jerúsálémù; Jóṣéfù àti ìyá rẹ̀ kò mọ̀.

44. Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe bí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ èrò, wọ́n rin ìrìn ọjọ́ kan; wọ́n wá a kiri nínú àwọn ará àti àwọn ojúlùmọ̀ wọn.

45. Nígbà tí wọn kò sì rí i, wọ́n padà sí Jerúsálémù, wọ́n ń wá a kiri.

46. Ó sì ṣe, lẹ́yìn ijọ́ mẹ́ta wọ́n rí i nínú tẹ́ḿpílì ó jòkòó ní àárin àwọn olùkọ́ni, ó ń gbọ́ ti wọn, ó sì ń bi wọ́n léèrè.

47. Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ fún òye àti ìdáhùn rẹ̀.

48. Nígbà tí wọ́n sì rí i, háà ṣe wọ́n: ìyá rẹ̀ sì bi í pé, “Ọmọ, èéṣe tí ìwọ fi ṣe wá bẹ́ẹ̀? Sá wò ó, bàbá rẹ̀ àti èmi ti ń fi ìbìnújẹ́ wá ọ kiri.”

Lúùkù 2