Lúùkù 2:23-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. (Bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Olúwa pé, “Gbogbo ọmọ ọkùnrin tí ó ṣe àkọ́bí, òun ni a ó pè ní mímọ́ fún Olúwa”),

24. àti láti rúbọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí a wí nínú òfin Olúwa: “àdàbà méjì tàbí ẹyẹlẹ́ méjì.”

25. Sì kíyèsí i, ọkùnrin kan wà ní Jerúsálémù, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Ṣíméónì; ọkùnrin náà sì ṣe olóòótọ́ àti olùfọkànsìn, ó ń retí ìtùnú Ísírẹ́lì: Ẹ̀mí mímọ́ sì bà lé e.

26. A sì ti fihàn án láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ náà wá pé, òun kì yóò rí ikú, kí ó tó rí kírísítì Olúwa.

27. Ó sì ti ipa Ẹ̀mí wá sínú tẹ́ḿpìlì: nígbà tí àwọn òbí rẹ̀ sì gbé ọmọ náà Jésù wá, láti ṣe fún un bí ìṣe òfin,

28. Nígbà náà ni Símọ́nì gbé e ní apá rẹ̀, ó fi ìbùkún fún Ọlọ́run, ó ní:

Lúùkù 2