Lúùkù 12:49-53 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

49. “Iná ni èmi wá láti sọ sí ayé; kínni èmi sì ń fẹ́ bí kò ṣe kí a ti dá a ná!

50. Ṣùgbọ́n èmi ní bamtísíìmù kan tí a ó fi bamitisí mi; ara ti ń ni mí tó títí yóò fi parí!

51. Ẹ̀yin ṣe bí àlààáfíà ni èmi wá fi sáyé? Mo wí fún yín, Bẹ́ẹ̀ kọ́; ṣùgbọ́n bí kò ṣe ìyapa.

52. Nítorí láti ìsinsìn yìí lọ, ènìyàn márùn-ún yóò wà ní ilé kan náà tí a ó yà ní ipa, mẹ́ta sí méjì, àti méjì sí mẹ́ta.

53. A ó ya baba nípa sí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ ọkùnrin sí baba; ìyá sí ọmọbìnrin, àti ọmọbìnrin sí ìyá rẹ̀, ìyá ọkọ sí ìyàwó ọmọ, àti ìyàwó ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀.”

Lúùkù 12