40. Ṣùgbọ́n Mátà ń ṣe ìyọnu ohun púpọ̀, ó sì tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Olúwa, ìwọ kò sì bìkítà sí ti arábìnrin mi pé ó fi mí sílẹ̀ láti máa nìkàn ṣe ìránṣẹ́? Wí fún un kí ó ràn mí lọ́wọ́.”
41. Ṣùgbọ́n Jésù sì dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Mátà, Mátà, ìwọ ń ṣe àníyàn àti làálàá nítorí ohun púpọ̀.
42. Ṣùgbọ́n ohun kan ni a kò lè ṣe aláìní, Màríà sì ti yan ipa rere náà tí a kò lè gbà lọ́wọ́ rẹ̀.”