Léfítíkù 26:15-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Bí ẹ̀yin bá kọ àṣẹ mi tí ẹ̀yin sì kórira òfin mi, tí ẹ̀yin sì kùnà láti pa ìlànà mi mọ́, nípa èyí tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ sí májẹ̀mú mi.

16. Èmi yóò se àwọn nǹkan wọ̀nyí sí yín: Èmi yóò mú ìpáyà òjijì bá yín: àwọn àrùn afinisòfò, àti ibà afọ́nilójú, tí í pani díẹ̀díẹ̀. Ẹ̀yin yóò gbin èso ilẹ̀ yín lásán: nítorí pé àwọn ọ̀ta yín ni yóò jẹ gbogbo ohun tí ẹ̀yin ti gbìn.

17. Èmi yóò dojú kọ yín títí tí ẹ̀yin ó fi di ẹni ìkọlù; àwọn tí ó kóríra yín ni yóò sì ṣe àkóso lórí yín. Ìbẹ̀rù yóò mú yín débi pé ẹ̀yin yóò máa sá kákìkiri nígbà tí ẹnikẹ́ni kò lé yín.

18. “ ‘Bí ẹ̀yin kò bá wá gbọ́ tèmi lẹ́yìn gbogbo èyí: Èmi yóò fi kún ìyà yín ní ìlọ́po méje nítorí ẹ̀ṣẹ̀ yín.

19. Èmi yóò fọ́ agbára ìgbéraga yín: ojú ọ̀run yóò le koko bí irin: ilẹ̀ yóò sì le bí idẹ (òjò kò ní rọ̀: ilẹ̀ yín yóò sì le).

Léfítíkù 26