Jóṣúà 6:25-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Ṣùgbọ́n Jóṣúà dá Ráhábù asẹ́wó pẹ̀lú gbogbo ìdílé e rẹ̀ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tirẹ̀ sí nítorí pé, ó pa àwọn ọkùnrin tí Jóṣúà rán gẹ́gẹ́ bí ayọ́lẹ̀wò sí Jẹ́ríkò mọ́. Ó sì ń gbé láàrin ará Ísírẹ́lì títí di òní yìí.

26. Ní àkókò náà Jóṣúà sì búra pé; “Ègún ni fún ẹni náà níwájú Olúwa tí yóò dìde, tí yóò sì tún ìlú Jẹ́ríkò kọ́:“Pẹ̀lú ikú àkọ́bí ọmọ rẹ̀ niyóò fi pilẹ̀ rẹ̀;ikú àbíkẹ́yìn in rẹ̀ ní yóò figbé ìlẹ̀kùn bodè rẹ̀ ró.”

27. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wà pẹ̀lú Jóṣúà; òkìkí rẹ̀ sì kàn ká gbogbo ilẹ̀ náà.

Jóṣúà 6