Jóṣúà 5:8-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Lẹ́yìn ìgbà tí gbogbo orílẹ̀ èdè náà kọ ilà tan, wọ́n dúró ní ibi tí wọ́n wà ní ibùdó títí ilà wọn fi jinná.

9. Nígbà náà ní Olúwa wí fún Jóṣúà pé, “Ní òní ni mo yí ẹ̀gàn Éjíbítì kúrò ní orí yín.” Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní Gílígálì títí ó fi di òní yìí.

10. Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹ́rìnlá (14) oṣù náà (oṣù kẹ́rin) (4) nígbà tí wọ́n pàgọ́ ní Gílígálì ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jẹ́ríkò, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì ṣe ọdún Àjọ-ìrékọjá.

11. Ní ọjọ́ kéjì Àjọ-ìrékọjá, ní ọjọ́ náà gan-an ni, wọ́n jẹ nínú; àwọn irè oko ilẹ̀ náà: àkàrà aláìwú, àti ọkà yíyan.

12. Mánà náà sì tan ní ọjọ́ kéjì tí wọ́n jẹ oúnjẹ tí ilẹ̀ náà mú jáde; kò sì sí mánà kankan mọ́ fún àwọn ará Ísírẹ́lì, ṣùgbọ́n ní ọdún náà wọ́n jẹ irè oko ilẹ̀ Kénánì.

13. Nígbà tí Jóṣúà sún mọ́ Jẹ́ríkò, ó wo òkè ó sì rí ọkùnrin kan tí ó dúró ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú idà ní ọwọ́ rẹ̀. Jóṣúà sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bi í pé, “Ǹjẹ́ ìwọ wà fún wa tàbí fún ọ̀ta a wa?”

Jóṣúà 5