9. Jóṣúà sì sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé, “Ẹ súnmọ́ ibí, kí ẹ̀yin kí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín.
10. Èyí ni ẹ̀yin yóò fi mọ̀ pé Ọlọ́run alààyè wà ní àárin yín àti pé dájúdájú yóò lé àwọn ará Kénánì, àwọn ará Hítì, Hífì, Pérésì, Gágáṣì, Ámórì àti Jébúsì jáde níwájú u yín.
11. Àpótí ẹ̀rí Olúwa gbogbo ayé, ń gòkè lọ sí Jọ́dánì ṣáájú u yín.