Jóṣúà 3:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní kùtùkùtù òwúrọ̀, Jóṣúà ati gbogbo àwọn Ísírẹ́lì sí kúrò ní Sítímù, wọ́n sì lọ sí etí odò Jọ́dánì, wọ́n sì pa ibùdó síbẹ̀ kí wọn tó kọjá.

2. Lẹ́yìn ọjọ́ kẹ́ta àwọn olórí la àárin ibùdó já.

3. Wọ́n sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé: “Nígbà tí ẹ bá rí àpótí i májẹ̀mú Olúwa, Ọlọ́run yín, tí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Léfì rù ú, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sí kúrò ní ipò o yín, ẹ̀yin yóò sì máa tẹ̀lé e.

4. Ẹyin yóò lè mọ ọ̀nà tí ẹ ó gbà, torí pé ẹ̀yin kò gba ọ̀nà yìí tẹ́lẹ̀ rí. Ṣùgbọ́n àlàfo gbọdọ̀ wà ní àárin yín àti àpótí náà, tó bí ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún un mítà (1000).”

Jóṣúà 3