11. Ìbò náà sì wá sórí ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì, ní agbo ilé, agbo ilé. Ilẹ̀ ìpín wọn sì wà láàárin ti ẹ̀yà Júdà àti Jósẹ́fù:
12. Ní ìhà àríwá ààlà wọn bẹ̀rẹ̀ ní Jọ́dánì, ó kọjá lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Jẹ́ríkò ní ìhà àríwá, ó sì forílé ìwọ̀-oòrùn sí ìlú òkè, jáde sí asálẹ̀ Bẹti-Áfẹ́nì.
13. Láti ibẹ̀ ààlà náà tún kọjá lọ sí ìhà gúsù ní ọ̀nà Lúsì, (èyí ni Bẹ́tẹ́lì) ó sìdé Afaroti-Ádárì, ní orí òkè tí ó wà ní gúsù Bẹti-Hórónì
14. Láti òkè tí ó kọjú sí Bẹti-Hórónì ní gúsù ààlà náà yà sí gúsù ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó sì jáde sí Kiriati-Báálì (tí í ṣe Kiriati-Jéárímù), ìlú àwọn ènìyàn Júdà. Èyí ni ìhà ìwọ̀-oòrùn.
15. Ìhà gúsù bẹ̀rẹ̀ ní ìpẹ̀kun Kiriati-Jéárímù ní ìwọ̀-oòrùn, ààlà náà wà ní ibi ìsun omi Nẹ́fítóà.