Jóṣúà 17:1-2 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èyí ní ìpín ẹ̀yà Mànásè tí í ṣe àkọ́bí Jósẹ́fù, fún Mákírì, àkọ́bí Mánásè. Mákírì sì ni babańlá àwọn ọmọ Gílíádì, tí ó ti gba Gílíádì àti Básánì nítorí pé àwọn ọmọ Mákírì jẹ́ jagunjagun ńlá.

2. Nítorí náà ìpín yìí wà fún ìyókù àwọn ènìyàn Mánásè: ní agbo ilé Ábíésérì, Hélékì, Ásíríélì, Sékémù, Héférì àti Ṣémídà. Ìwọ̀nyí ní àwọn ọmọ ọkùnrin Mánásè ọmọ Jósẹ́fù ní agbo ilé wọn.

Jóṣúà 17