Jóṣúà 13:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà tí Jóṣúà sì darúgbó tí ọjọ́ orí rẹ̀ sì pọ̀ jọjọ, Olúwa sọ fún un pé, “Ìwọ ti darúgbó púpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ilẹ̀ sì kù lọ́pọ̀lọpọ̀ fún yín láti gbà.

2. “Èyí ni ilẹ̀ tí ó kù: gbogbo àwọn agbègbè àwọn Fílístínì, àti ti ara Gésúrì:

3. láti odò Ṣíhónì ní ìlà oòrùn Éjíbítì sí agbégbé Ékírónì ìhà àríwá, gbogbo rẹ̀ ni a kà kún Kénánì (agbégbé ìjòyè Fílístínì márùnún ní Gásà, Ásídódù, Áṣíkélónì, Gátì àti Ékírónì ti àwọn ará Áfítì):

4. láti gúsù, gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Kénánì, láti Árà ti àwọn ará Sídónì títí ó fi dé Áfékì, agbègbè àwọn ará Ámórì,

Jóṣúà 13