Jóṣúà 10:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní báyìí tí Adoni-Sédékì ọba Jérúsálẹ́mù gbọ́ pé Jóṣúà ti gba Áì, tí ó sì ti pa wọ́n pátapáta; tí ó sì ṣe sí Áì àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Jẹ́ríkò àti ọba rẹ̀, àti bí àwọn ènìyàn Gíbíónì ti ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú Ísírẹ́lì, tí wọ́n sì ń gbé nítòsí wọn.

2. Ìbẹ̀rù sì mú òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀ torí pé Gíbíónì jẹ́ ìlú tí ó ṣe pàtàkì, bí ọ̀kan nínú àwọn ìlú ọba; ó tóbi ju Áì lọ, gbogbo ọkùnrin rẹ̀ ní ó jẹ́ jagunjagun.

3. Nítorí náà Adoni-Sédékì ọba Jérúsálẹ́mù bẹ Hóámù ọba Hébúrónì, Pírámù ọba Jámútù, Jáfíà ọba Lákíṣì àti Débírìe ọba Égílónì. Wí pe,

Jóṣúà 10