Jóòbù 31:8-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Ǹjẹ́ kí èmi kí ó gbìn kí ẹlòmìírànkí ó sì mújẹ, àní kí a fa irú ọmọ mi tu.

9. “Bí àyà mi bá di fífà sípasẹ̀ obinrin kan,tàbí bí mo bá lọ í ba de ènìyàn ní ẹnu ọ̀nà ilé aládùúgbò mi,

10. Ṣùgbọ́n kí àyà mi kí ó lọ ọlọ fúnẹlòmíràn, kí àwọn ẹlòmíràn kí ó tẹ̀ ara wọn ní ara rẹ̀.

11. Nítorí pé yóò jẹ́ ohun ìtìjú àníẹ̀ṣẹ̀ tí a ó ṣe onídàájọ́ rẹ̀

12. Nítorí pé iná ní èyí tí ó jó dé ibiìparun, tí ìbá sì fa gbòǹgbòohun ìbísí mi gbogbo tu.

13. “Tí mo bá sì se àìka ọ̀ràn ìránṣẹ́kùnrinmi tàbí ìránṣẹ́bìnrin mi sí, nígbà tí wọ́n bá ń bá mi jà;

Jóòbù 31